Ori Kàrún

1 Wọ̀n wá sí apa´keji`òkun, sí agbègbè àwọn Kérásènè. 2 Nígbàtí Jésù sí jáde kúrò nínú ọkọ̀ ojú omi, lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀ ọkuǹrin kan sí tọ̀ wá láti inù isà-okú tí óní èmi'-àimọ. 3 Ọkùnrin náà ma ńgbé nínú isà-òkú . Kò sì si ẹni tí o le dìímú, koda pelu ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀. 4 Wón ti ma ń dé è lọ́pọ̀lọpọ̀ ìgbà pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ ní ọwọ́ àtì ẹsẹ̀. Ọkùnrin yìí má ń gé ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ tọwọ̀ atì tẹsẹ̀ sí wẹ́wẹ́. kòsí sí ẹni tí agbára rẹ̀ káa. 5 Ní gbogbo ọ̀sán àti òru ni isà-òkú àti ní àwọn orí-òkè, Ó ma ń pariwo jáde Ó si ma tún ya ara rẹ̀ lára pẹ̀lú àwon òkúta tí ó mú. 6 Nígbàtí ó rí Jésù láti jìnnàjìnnà, ó sáré si, o sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀. 7 Ó pariwo jade lohùn rara, "Ki ni mo ni se pẹ̀lú rẹ, Jésù Ọmọ Ọlọ́run ọ̀gá ògo? Mo bẹ Ọ lórúkọ̀ Ọlọrun nìkan, máse fòró mi." 8 Nítorí ti O ti ń sọ fún "jáde kúrò lára ọkúnrin náà, ìwọ ẹ̀mi àìmọ́." 9 Ó sì bi lere, "Kínni orúko re?" Ó da lóhùn wípé, "Orúko mi ni Lígíónì, nítorí wípé a pọ̀." 10 O bẹ̀, o sì tún bẹ ẹ, láti ma lé àwọn kúrò ní agbègbè náà. 11 Ó sì se, agbo àwọn ẹlẹ́dẹ̀ sì jẹun lórí òkè, 12 Wọ́n sì bẹ́ẹ̀, wípé, "Rán wa lọ sí inú agbo ẹlẹ́dẹ̀; kí a sì wọ inú wọn lọ." 13 Ó sì gbà wọ́n láyè; àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà sì jáde, wọ́n sì wọnù àwọn agbo ẹlẹ́dẹ̀ lọ, wọ́n sì sáré sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkun, bí ẹgbẹ̀rún méjì ẹlẹ́dẹ̀ si parun sínú òkun. 14 Àwọn tí ó fi oúnjẹ fún àwọn elẹ́dẹ̀ náà sí sálọ, wọ́n sí ròyìn ohun tí ó sẹlẹ̀ lárin ìlú àti ní gbogbo agbègbè, àwọn ènìyàn sì jáde láti rí ohun tí ó sẹlẹ̀. 15 Àwon ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ Jésù, wọ́n sì rí ọkùnrin ẹlẹ́mìí àìmọ́ náà, èyí tí ó kún fún Lígíónì, ó jóko pẹ̀lú ẹ̀wù lọ́rùn àti ọpọlọ tó yè koro. 16 Àwọn tí ó sì rí ohun tí ó sẹlẹ̀ sí ọkùnrin ẹlẹ́mì àìmọ́ náà ròyìn ohun tí ó sẹlẹ̀ ní kíkún fún wọn, wọ́n sì ròyìn fún wọn nípa ohun tí ó sẹlẹ̀ sí àwon ẹlẹ́dẹ̀. 17 Nígbànà ní wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sì ní bẹ̀ pé kó fi agbègbè àwọn sílẹ̀. 18 Nígbàtí ó wọnú ọkọ̀ ojú omi lọ, ọkùnrin aláimọ́ náà bẹ̀ pé kí ohun le wà pẹ́lù rẹ. 19 Sùgbọ́n Jésù kò gbàá láyè, sùgbọ́n ó dá lóhùn wípé, "Lọ sí ilé rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn mọ̀lẹ́bí re, kí ó royin ohun tí Olúwa tí se fún ọ àti bí ó ti fi anu han si ọ. 20 Ó sì lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí polongo àwọn ohun ń la tí Jésù tí se fún ni agbègbé Dẹ́kápólísì, ẹnu sí yà gbogbo ènìyàn. 21 Nígbàtí Jésù tí re kojá sí òdì kejì, nínú ọkọ̀ ojú omi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yii ká, bí ó ti wà lẹgbẹ òkun. 22 Ọ̀kan nínú àwon olùdarí sínágọ́gú, ẹní tí orúkọ rẹ̀ ńjẹ́ Jáírù, ó wáà, nígbàtí ó sì ri, o wólẹ̀ níwájú rẹ̀. 23 Ó bẹ̀ ẹ́, ó sì tún bẹ̀ wípé, ọmọ mi obìnrin kékeré fẹ́rẹ̀ kú. Mo bẹ̀ Ọ́, wá dá ọwọ́ rẹ lee kí ó le padà bọ̀ sí pò kí o sì wà ní àláfíà. 24 Nítorína Ó bá lo. ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì ba lọ àti pé wọ́n súmọ́ Ó pẹ́kípẹ́kí ní agbègbè náà. 25 Obìnrin kan sí wá ní bẹ tí o ní isun ẹ̀jẹ̀ fún ọdún méjìlá. 26 Ó tí ní orísiríìsi ìlàkọjá pẹ̀lú àwon onísègùn àti pé ó ti ná ohun gbogbo tí óní, sùgbọ́n, kàkà kí o sàn se ló ń le koko si. 27 Nígbàtí o sì gbó ìròyìn nípa Jésù, ò sí tọ̀ wá larin àwon èrò, ò dúró lẹ́yìn rẹ̀, ó sì fi ọwọ́ kan etí asọ Rẹ̀. 28 Nítorí tí ó wípé, "tí mo bá le fọwọ́ kan etí asọ Rẹ̀, èmi yóò gba ìwòsàn. 29 "Nígbàtí o fọwọ́ kan, ìsun ẹ̀jẹ̀ náà dáwọ́ dúró, ó sì mọ̀ lára rẹ̀ wípé ìsun ẹ̀jẹ̀ náà tí dáwọ́ dúró, pé ohun ti rí ìwòsàn nínú gbogbo ìdàmù náà. 30 Jésù sì ní ìmọ̀lára lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀ wípé agbára ti jáde kúrò lára òhun. Ó wò yíká láàrín èrò wípé, "tani ó fọwọ́ kan asọ mi?". 31 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Rẹ̀ wí fún pé, "O ri bi àwọn ènìyàn yìí tí yípo Rẹ, ó sì ni, "tani ó fọwọ́ kàn mí?" 32 Jésù wò yíká láti rí ẹni tó ṣe eléyìí. 33 Obìnrin náà, nítorí ó mọ ohun tí ó sẹlẹ̀, ó si bẹ̀rù pẹ̀lú ìwárìrì. Ó wa, ó sì kùnlẹ́ níwáju Rẹ̀, ò sí sọ òtítọ́ fún ún. 34 Ò sí wí fun pè, "Obìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá. Ma lọ lalafia ki o si gba ìwòsàn kúrò nínú àrùn rẹ. 35 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, àwọn kan wá láti ọ̀dọ̀ olórí sínágọ́gú, wípé "Ọmọ rẹ obìnrin ti kú, kí ló dé tí ó ńyọ Olùkóni lẹ́nu?" 36 Nígbàtí ohun tí wọ́n sọ dé etí ìgbo Jésù, Ó sọ fún olórí sínágọ́gú pé "Má bẹ̀rú, ìwọ sá gbàgbó". 37 Kò si gba ẹnikẹ́ni laye láti tẹ̀le, àyàfi Pétérù, Jákọ́bù ati Jòhánù arákùnrin Jákọ́bù. 38 Wọ́n sì wá sí ilé olórí sínágọ́gú, Ó sì ri àwọn ènìyàn tí wọ́n pariwo; wọ́n sọkún, wọ́n sì ké rora sókè. 39 Nígbàtí Ò sí wọ ilé náà, Ó wí fún wọ́n wípé, "Kí lódé tí ẹ ń banújẹ́ tí ẹ ṣì ńsọkún? Ọmọ náà kò kú, sùgbọ́n ó sùn." 40 Wọ́n sì fi rẹ́rin. Sùgbọ́n Ó ti gbogbo wọ́n si ta. Ó sì mu baba ọmọ náà, ìyá ọmọ náà àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, Ó sì wọ́lè sí ibi tí ọmọ náà wa. 41 Ó sì mu ọwọ́ ọmọ náà Ó sì wí fún wípé, "Talitha Koum!" èyí tí ó túmọ̀ sí wípé, "ọmọbìnrin, mo wí fún ọ, dìdé." 42 Lójú kanáà, ọmọ náà didé, ó sì ń rìn (Ó jé ọmọ ọdún méjìlá nigbana). Lẹ́sẹ̀kánnà ẹnu yà wọ́n, ìbẹ̀rù bojo sì mú ọkàn wọn. 43 Ó sì pàsẹ fún wọn wípé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ mọ̀ ní pa rẹ̀. Ó sì wí fún wọn wípé, kí wọn fun lóúnjẹ jẹ.