Ori Kefa

1 Ó sì jáde lọ sí ìlú abínibí rẹ̀, àwọn ọmọ ẹ̀yin rẹ̀ sì tẹ̀ le. 2 Nígbàtí ódi ọjọ́ Ìsinmi, Ó nkọ́ wọn nínú sínágógù. Òpò ènìyàn sì gbọ́ ẹ̀kọ́ náà, ẹnú sì yà wọ́n. Wọ́n sì bèèrè wípé, "níbo ni o ti rí gbogbo ẹ̀kọ́ tí ò ń kọ́ ni yí?" "Irú ọgbọ́n wo ni afi fún yìí?" "Irú àwọn isẹ́ ìyanu wo ni ó ń fi ọwó rẹ̀ se wọ̀nyí?" 3 "Sẹ́ kìí se gbénàgbénà náà nì yí, ọmọ bíbí Màríà, àti arákùnrin Jémìsì, àti Jósè, àti Júdà, àti Símónì? Sebí àwọn arábìrin rẹ̀ ń gbé pẹ̀lu wa?" Inú Jésù sì bí wọn. 4 Jésù sì wí fún wọn pé, "Wôlí kìí sa láì lọ́lá, àyàfi lárin ìlú rẹ̀, àti lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, àti nínú ilé rẹ̀." 5 Kò sì le sisẹ́ ìyanu lárin wọn, Ó kàn gbé ọwọ́ lé àwọn aláìsàn díẹ̀, Ó sì wò wón sàn. 6 Ẹnú sì yàá nítorí àìgbàgbọ́ wọn, Ó sì jáde lọ sí àwọn abúlé láti kọ́ wọn. 7 Ó sì pe àwọn méjìlá, Ó rán wọn jáde ní méjì méjì, Ó sì fún wọn ní agbára lórí àwọn ẹ̀mí àìmọ́. 8 Ó wí fun wọn pé; ẹ kò gbọdọ̀ mú ohun kóhun dání fún ìrìnàjò yí, bíkòse ọ̀pá ìtìlẹ̀ yín, ẹ kògbọdọ̀ mú àkàrà tàbí gbé àpó tàbí mú owó sínú ìgbàdí. 9 Sùgbọ́n, kí wọn kí o wọ bàta, kí wọ́n má sì mú asọ míràn dání. 10 Ó sì wí fún wọn pé, "ilékílé tí ẹbá wọ̀, níbẹ̀ nikí ẹ dúró sí dìgbà tí ẹbá kúrò ní ìlú náà. 11 Tí ìlú kan kò bá gbà yín tàbí tí wọ́n kò tẹ́tí sí ẹ̀kọ́ yín, nígbà tí ẹ bá kúrò níbẹ̀, kí ẹ sì gbọn eruku ẹsẹ̀ yín síbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí sí wọn." 12 Wọ́n sì jáde lọ láti kéde pé kí àwọn ènìyàn yípadà kúrò nínú ẹ̀sẹ̀ wọn. 13 Wọ́n lé àwọn ẹ̀mí èsù jáde, wọ́n fi òróró kun àwọn aláìsàn wọ́n sì gba ìmúláradá. 14 Ọba Ẹ́rọ́dù sì gbọ́, nítorí ìròyìn Jésù tàn ká. Àwọn kán nwípé "Jòhánà Onítẹ̀bọmi ti jí dìde, ìdí nìyí tí isẹ́ agbára fí nsẹlẹ̀ láti ọwọ́ rẹ̀. 15 Àwọn míràn sì wípé"Èlíjà ni." Bẹ́ẹ̀ ni àwọn míràn sì wípé "ọ̀kan nínú àwọn wǒlí àtijọ́ ni." 16 Sùgbọ́n nígbàt´ Hẹ́rọ́dù gbọ́ èyií, ó wípé "Jòhánù tí mo gé orí rẹ̀, ti jí dìde." 17 Nítorí Hẹ́rọ́dù ránṣẹ́ láti mú Jòhánù, ó sì jú sẹ́wọ̀n nítorí Hẹrodíà, aya arákùnrin rẹ̀ Fílípì tí ó yàn lálè. 18 Nítorí Jòhánù bá Hẹ́rọ́dù wí, "pé kò tọ̀nà láti yan aya arákùnrin rẹ̀ lálè." 19 Hẹrọdíà sì bínú sí Jòhánù, ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á, èyí sì nira fún 20 nítorí Hẹ́rọ̀dù bẹ̀ru Jòhánù. Àti wípé ó mọ̀n pé olódodo àti ènìyan mímó ni, ó sì pa á mọ́n. Gbígbọ́ ọ̀rọ rẹ̀ má ń bíi nínú, sùgbọ́n ó má n fi ayọ̀ gbọ́ ọ. 21 Àǹfàní láti pa á wá nígbàtí Ọba Hẹ́rọ́dù se ọjọ́ ìbí, ósì se àsè fún àwọn ẹmẹ̀wà rè, àwọn aláṣẹ àti awọn adarí ní ilẹ́ Gálílì. 22 Ọmọbìrin Hẹrọdíà sì wá fi ijó dá Hẹ́rọ́dù àti àwọn àlejò rẹ̀ lárayá. ẹ́ba Hẹ́rọ́dù sì wípé fún omobìrin náá pé: "bèrè ohun kóhun tí o bá fẹ́ ní ọwọ́ mi, emí ó sì fi fún ọ." 23 Hẹ́rọ́dù sì búra f´n ọ̀dọ́mọbìrin náà pé, "ohun kóhun tí ó bá fẹ́ títí dé ìdajì ìjọba mi, ni èmi ó fifún ọ. 24 Ọmọbìrin yì sì lọ bèèrè lọ́wọ́ ìya rẹ̀ wípe; "kí ni kín bèrè?" Ó sì wí fún pé, "bèrè orí Jòhánù Onítẹ̀bọmi." 25 Ó sì ṣáré padà wá bá ọba, ó sì bèèrè wípé, "Mo fẹ́ orí Jòhánù Onítẹ̀bọmi nísisìyí sínú igbá yí." 26 Bó tilẹ̀ jẹ́ wípé èyí ba ọba nínú jẹ́, kò le sa láì mú ìbéèrè rẹ̀ se nítorí tí óti búra fún un àti nítorí àwọn àlejò rẹ̀. 27 Ọba rán àwọn emèwà rẹ̀ kí wọ́n lọ bẹ́ orí Jòhánù wá. Ẹmẹ̀wà náà sì lọ bẹ́ orí Jòhánù láti inú ọgbà ẹ̀wọ̀n wá 28 Ósì gbẹ́ fún ọ̀dọ́mọbirin náà nínú igbá, ọmọbìrin náà sì lọ gbè e fún ìya rẹ̀. 29 Nígbàtí àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ gbọ́, wọ́n lọ gbé ara rẹ̀ tókù lọ sí ibojì. 31 30 30 Àwọn àpóstélì padà tọ Jésù wá wọ́n sì sọ fún gbogbo inkàn tí wọ́n ti ṣe àti tí wọ́n ti kọ́. Ó sì ṣọ fún wọn pé" Ẹ wá fún ra yín sínú ijú kí ẹ sì sinmi díẹ̀ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni wọ́n lọ tí wọ́n bọ̀ láì ní ààyè láti jẹun. 32 Bẹ́ẹ̀ni wọ́n lọ kúrò nínú ọkọ̀ ojú omi sínú aginjù láti sinmi. 33 33 Sùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i tí wọ́n lọ àwọn púpọ̀ dáwọn mòn,wọ́n sì ṣáré pèlu ẹṣẹ̀ láti gbogbo ìlú wọ́n sì síwájú wọn dẹ́ ibè. 34 Nígbàtí wọ́n dé èbúté, ó rí èrò púpọ̀ ànú rẹ̀ sì ṣe wọ́n, nítorí tí wọ́n dàbi àgùtàn tí kòní olùṣọ́. Bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀ẹ̀rẹ̀ síní kọ́ wọn. 35 35 Nígbàtí ọjọ́ ti lọ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀,wọ́n sì wípé "Inú ijù ni èyí ilẹ̀ sì ti sú. 36 Rán wọn lọ, kí wọn kí ó lọ sí ìlú tí ó súnmọ́n àti ìgbèríko, kí wọn kí ó lọ ra ohun tí wọn yóò jẹ fún ara wọn. 37 Ó sì dáhùn ó wí fún wọn pé " Ẹ fún wọn ní ohun tí wọn yóò jẹ.Wọ́n ṣọ fún un pé,"Sé a le lọ ra àkàrà ní ìwọn igba dénárì kí á sì fún wọn kí wọ̀n jẹ. 38 Ó bi wọ́n pé isu ìwọn àkàrà měló lẹ ní? Ẹ lọ wò ó," Nígbàtí wọ̀n rì, wọ́n ní "Ìsù àkàrà mǎrún àti ẹja méjì" 39 Ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọ́n jókòó ní ìsòrí ìsòrí lórí koríko tútù. 40 Wọ́n sì jókòó ní ìṣọ̀rí ọgọ́rọ̀rún àti àràdọ́ta. 41 Ò sì mú ìsù àkàrà mǎrún àti ẹja méjì náà, ó gbójú sókè ọ̀run ó yà sí mímó ó sì fún àwọn ọmọ ẹ̀yin rẹ̀ pé kí wọn kí ó pín fún àwọn ènìyàn náà. 42 Gbogbo wọn jẹun títí tí wọ́n fi yó. 43 Wón sì kó mí àjẹkù agbọ̀n méjìlà . 44 Iye àwọn tí ó jẹ ìsù àkàrà náà ní se ẹgbẹ̀rún mǎrún. 45 Lójijì ni ó ní kí àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ọkọ̀ ojú omi kí wọ́n sì síwájú rẹ̀ lọ sí apákejì lọ sí Bẹtisáídà, nígbà tí ó rán mí àwọn ìjọ ènìyàn lọ. 46 Nígbàtí wọ́n sì ti lọ, ó lọ sí orí òkè lọ gbàdúrà. 47 Ní gbà tí ó di àṣálẹ́, ọkọ̀ ojú omi náà sì wà nì àrin òkun, òun nìkán sì wà nílẹ̀ 48 49 Ó rí i pé ìjì se ọwọ́ ódì síwọn wọ́n sì dààmú níwọn bí ìṣọ̀ kẹrin òru,ó wá bá wọn ó ń rìn lórí òkun, ó sì fẹ́ kọjá wọn. Sùgbọ́n nígbàtí wn rí i tí ó ń rìn lórí omi, wọ́n rò wípé iwin ni, wọ́n kígbe sókè. 50 nígbàtí wọ́n rí i,ẹ̀rù bàwọ́n. Lọ́gán ni ó bá wọn ṣọ̀rọ̀ tí ó sọ wípé "Ẹse gírí! È mi ni Ẹ má bẹ̀rù!" 51 Ó wọ inú ọkò ojú omi pẹ̀lu wọn, ìjì náà sì dákẹ́jẹ́. Ẹnú sì yà wọ́n gidigidi. 52 Nítorítí wọn ko ti mon ohun tí àkàrà tú mọ̀n sí dípò ọkàn wọ́n le. 53 Nígbàtí wọ́n sì ti rékọjá, wọ́n wá sí ilẹ̀ Généṣárẹ́tì, wọ́n sì tu ọkọ̀ ojú omi. 54 Nígbàtí wn sì jáde kúrò nínú ọkọ̀ ojù omi náà, àwọn ènìyàn dá mọ̀n lọ́gán, 55 wọ́n sí sáré kiri gbogbo agbègbè náà láti lọ gbé àwọn aláìsàn wá lórí akètè wọn sí ibikíbi tí wọ́n gbọ̀ pé ó wà. 56 Nígbákúgbà tí ó bá wọ ìletò, ìlù tàbí orílè èdè, wọ̀n ń gbé àwọn aláìsán wá láti inú ọjà. Wọ́n bẹ̀ẹ́ kí wọn kí o le fọwọ́kan ìṣẹ́tì aṣọ rẹ̀, iye àwọn tí ó fọwọ́kǎn ni a mú láradá.